Ọ̀JỌ̀GBỌ́N ỌLÁBÍYÌÍ BABALỌLÁ YÁÌ NÁÀ TÚN TI LỌ!
Ọjọ́ wo la ó mẹbọ ikú?
Ẹ dákun, ìgbà wo la ó mètùtù àlùmúútù?
Nígbà wo la ó le pinkú nípá?
Tíkú á sinmi fáàrí ìmẹ́ni wa.
Òkèèrè ni mo ti mọ Ọ̀jọ̀gbọ́n Yai,
Àmọ́ ẹ̀ẹ̀mẹtẹ̀ẹ̀ta tí a sọ̀rọ̀ ni wọ́n bá mi sọ̀rọ̀ bí i Baba sí ọmọ.
Bí Bàbá mi Diípọ̀ Fágúnwà àti ìyá mi Yinka Adeboye ti ṣe ròyin wọn gẹ́lẹ́ ni wọ́n rí.
Wọn ò kìí yẹ àdéhùn àfi bí ohun mìíràn bá fa ìdíwọ́, wọn yóò sì fi àyípadà náà tóni létí.
Wọn ò kì ń fojú kéré ẹni, bí wọ́n ṣe jẹ́ àgbà Ọ̀jọ̀gbọ́n tó, síbẹ̀ wọn ò níwà ìfojú panirẹ́.
Inú oṣù kẹrin ọdún yìí ni a jọ ṣe àdéhùn pé a ó rí ra bí wọ́n bá wá sí Naijiria.
Kòrónà ló yẹ àdéhùn tí n kò fi làǹfààní láti rí wọn mọ́.
Inú Oṣù Kẹfà ni wọ́n sọ pé kí n jẹ́ ká pa ọkàn pọ̀ sọ́dún tó ń bọ̀,
Ọ̀jọ̀gbọ́n Yai ní kí n máa ṣiṣẹ́ tèmi lọ a ó máa ríra lọ́dún 2021,
Òní ọjọ́ karùn-ún oṣù Kejìlá Ọdún 2020 lỌ̀jọ̀gbọ́n pàtàkì juwọ sáyé.
Èyí dùn mi wọnú eégún,
Ó kan mí lára wọnú bọ́ọ́gọ́,
Àìṣeémú ikú ló jẹ́ n gba kámú.
Kí Ọlọ́run ó tẹ́ wọn sí afẹ́fẹ́ rere,
Kí gbogbo ohun tí wọ́n fi sílẹ̀ ó má bàjẹ́ láṣẹ Èdùmàrè.
✍️Bùkọ́lá R. Adélékè (2020)
(Ìṣẹ̀dálẹ̀ Media Concept)